Tiktok @storiesfromafrica YouTube @universalhertagetnnaija

(a lo àwọn fọ́nrán yí fún ẹ̀kọ́ nìkan, a sì ṣe ìdánimọ̀ fún àwọn tí ó ní ẹ̀tọ́ lórí rẹ̀.)

Gbọ Audio Ìròyìn Òmìnira

Ọ̀rọ̀ yìí dá lórí àwọn ète búburú tí Bill Gates ndáwọ́lé pẹ̀lú ìfọwọ́sowọ́pọ́ ìjọba agbésùnmọ̀mí Naijiria lórí àwọn ohun ọ̀gbin àgbélẹ̀rọ, àwọn amúnisìn yí tún ní èròngbà láti ṣe ikú pa àwọn dókítà ní ilé ìwòsàn àdáni káàkiri ìlú agbèsùnmọ̀mí Naijiria, wọn sí fẹ̀ ṣe àgbékalẹ̀ ilé iṣẹ́ ti yíò máa ṣe àgbélẹ̀rọ ẹ̀yà ara ènìyàn, pàápàá tí ẹ̀yà ara ènìyàn bá ní ààrùn, wọn kò fẹ́ lo òògùn sí mọ́, ṣugbọn wọn fẹ́ máa ṣe ẹ̀yà ara àgbélẹ̀rọ láti pààrọ̀ rẹ̀.

Bill Gates lò ní ilé iṣẹ́ yìí. Tí ènìyàn bá ní ààrùn ọkàn fún àpẹẹrẹ, dókítà á fi ẹ̀yà díẹ̀ lára ọkàn ẹni náà ránṣẹ́ sí ilé iṣẹ náà, wọ́n á wá yọ nkan nínú ọkàn náà láti paápọ̀ mọ́ ẹyin inú obìnrin láti ṣe ọkàn tuntun tí kò ní ààrùn, èyí ní wọn á dá padà fun dókítà láti fí sínú aláìsàn padà. Aláìsàn yìí yio san tó mílíọ̀nù kan sí méjì dọ́la tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ. Láti lè ṣe ọkàn ẹyọ kan wọ́n máa nílo mílíọ́nù lọ́nà ọgọ́run eyin obìnrin láti ara obìnrin bíi mílíọ̀nù mẹwa.

The Democratic Republic of the Yoruba also known in the Yoruba history as Yoruba Nation, Yoruba Kingdom, Yoruba Land and Yoruba Country is the newest nation in the world. The 55th nation in Africa and 17th in Western Africa as of 12th April 2024. Yoruba is know a sovereign nation and its no longer part of Nigeria.
Ìròyìn Òmìnira Olojoojumọ – Bèrè fún ẹ̀da títí rẹ!

Láti rí àwọn ẹyin yìí, Bill Gates tí ṣètò láti kọ́ ilé ìwòsàn bíi òjì-dín-ní-ọ̀ọ́dúnrún sí ìlú agbèsùnmọ̀mí Nàìjíríà láti máa fi yọ ẹyin nínú àwọn obinrin pẹ̀lú ẹ̀yà ara ènìyàn nípasẹ̀ pé Bill Gates ti wọ’nú àdéhùn búburú pẹlú ìjọba apanijayé Nàìjíríà láti máa yọ àwọn nkán wonyi lára ara ìlú wọn láì gbà àṣẹ lọ́wọ́ ẹnití ó ní ẹ̀yà ara náà. 

Fún àṣeyọrí iṣẹ́ ibí rẹ̀, Bill Gates ṣe ìpàdé pẹ̀lú àwọn àgbààgbà dókítà ilé ìwòsàn àdáni káàkiri ìlú agbèsùnmọ̀mí Nàìjíríà, ó fi owó gọbọi lọ̀ wọ́n pé kí wọ́n fí iṣẹ́ ìwòsàn ìlú agbèsùnmọ̀mí Naijiria sílẹ̀ fún òun kí àwọn dókítà náà gba òkè òkun lọ, ṣugbọ́n, wọ́n kọ̀ jálẹ́.

Nítorí kíkọ̀jálẹ̀ yí Bill Gates pinnu láti pa gbogbo àwọn dókítà aládáni náà patapata bí ó ti pa àwọn àgbẹ̀ tí ó ní irúgbìn àbáláyé ní òkè ọya, kí òun lè gba àkóso iṣẹ́ ìwòsàn ìlú agbèsùnmọ̀mí Naijiria, ó tún fọwọ́ sọ̀’yà fún àwọn dókítà náà pé gbogbo ilé ìwòsàn ìjọba agbésùmọ̀mí Naijiria ní òun tí rà pátápátá.

Àwa ọmọ ìbílẹ̀ Yorùbá (Indigenous Yorùbá People I.Y.P) ti Orílẹ̀ Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá (Democratic Republic of the Yorùbá D.R.Y), lóòtọ́ ni Olódùmarè ti lo màmá wa Olóyè Ìyá Ààfin Modupẹọla Onitiri-Abiọla láti kó wa jáde kuro lára ìlú agbèsùnmọ̀mí Naijiria, síbẹ wọn ṣì nfi agídí jẹ gàba lórí orílẹ̀-èdè wa, nítorínáà, màmá wa ti gbà wá níyànjú láti kíyèsára, ki a fà sẹhìn n’ílé ìwòsàn báyìí, kí á sì máa ṣe ìtọ́jú ara wa pẹ̀lú ewé àti egbò àwọn bàbá wa, kí á tún ṣọ́ra fún lílo òògùn òyìnbó pẹ̀lú abẹ́rẹ́ gbígbà.

Láì pẹ́ láì jìńnà, àwọn agbésùnmọ̀mí Nàìjíría tó ńfi agídí jẹ gàba lórí ilẹ̀ wa ni a ma ṣí nídìí, àwọn ìjọba Adelé wá máa lè tẹ̀síwájú iṣẹ́ ní oríkò ilé iṣẹ́ ìjọba wa, màmá wa fún wa ní ìdánilójú pé, gbogbo iṣẹ́ ibí àti iṣẹ́ ikú tí Bill Gates nṣe kíri kò ní ṣeé ṣe rárá nínú D.R.Y.